Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Látìgbà ìṣẹ̀lẹ̀ tó wáyé ní Pẹ́ńtíkọ́sì, lọ́dún 33 Sànmánì Kristẹni, nígbà tí ẹ̀sìn Kristẹni ṣẹ̀ṣẹ̀ fìdí múlẹ̀, ni Kristi ti ń ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí Ọba lórí ìjọ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ tá a fẹ̀mí yàn, tí wọ́n wà lórí ilẹ̀ ayé. (Kólósè 1:13) Nígbà tó di ọdún 1914, Ọlọ́run gbé àṣẹ lé Kristi lọ́wọ́ láti máa ṣàkóso lórí “ìjọba ayé.” Nítorí èyí, àwọn Kristẹni tá a fẹ̀mí yàn pẹ̀lú ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí ikọ̀ tí ń ṣojú fún Ìjọba Mèsáyà.—Ìṣípayá 11:15.