Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
g Ibí yìí ni Bíbélì ti bẹ̀rẹ̀ sí í pe Sọ́ọ̀lù ní Pọ́ọ̀lù. Àwọn kan sọ pé, torí Sájíọ́sì Pọ́lọ́sì ló ṣe bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ́ orúkọ Róòmù yìí. Àmọ́, Pọ́ọ̀lù ò yí orúkọ náà pa dà lẹ́yìn tó kúrò ní Sápírọ́sì, èyí jẹ́ ká rí i pé kì í ṣe torí Sájíọ́sì Pọ́lọ́sì ló ṣe ń jẹ́ orúkọ náà. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ló dìídì pinnu láti máa jẹ́ orúkọ yìí torí pé “àpọ́sítélì fún àwọn orílẹ̀-èdè” ni. Yàtọ̀ síyẹn, ó jọ pé ọ̀rọ̀ kan wà lédè Gíríìkì tó ní ìtumọ̀ tí ò dáa, tó sì jọ Sọ́ọ̀lù tó jẹ́ orúkọ Pọ́ọ̀lù lédè Hébérù. Torí náà, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ọ̀rọ̀ yìí ló mú kí Pọ́ọ̀lù pinnu pé òun ò ní jẹ́ Sọ́ọ̀lù mọ́.—Róòmù 11:13.