Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ó bọ́gbọ́n mu bí Jémíìsì ṣe fa ọ̀rọ̀ yọ látinú àwọn ìwé tí Mósè kọ. Ara àwọn ìwé náà ni Òfin Mósè àtàwọn àkọsílẹ̀ tó jẹ́ ká mọ ohun tó jẹ́ ìfẹ́ Ọlọ́run fáwa èèyàn kí Òfin Mósè tó dé. Bí àpẹẹrẹ, a lè rí àlàyé tó ṣe kedere nípa ojú tí Ọlọ́run fi ń wo ẹ̀jẹ̀, àgbèrè àti panṣágà nínú ìwé Jẹ́nẹ́sísì. (Jẹ́n. 9:3, 4; 20:2-9; 35:2, 4) Lọ́nà yìí, Jèhófà jẹ́ ká mọ àwọn ìlànà tó yẹ kí gbogbo èèyàn máa tẹ̀ lé, bóyá wọ́n jẹ́ Júù tàbí Kèfèrí.