c Ó dà bíi pé Kristẹni kan tó ń jẹ́ Títù wà lára àwọn tí wọ́n rán. Gíríìkì ni Títù, ó bá Pọ́ọ̀lù rìnrìn àjò nígbà tó yá, Pọ́ọ̀lù sì tún rán an lọ sáwọn ibì kan. (Gál. 2:1; Títù 1:4) Èèyàn dáadáa ni Títù. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Kèfèrí aláìdádọ̀dọ́ ni, Ọlọ́run fẹ̀mí yàn án.—Gál. 2:3.