Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Àwọn ọ̀mọ̀wé kan sọ pé àwọn ọkùnrin náà ti jẹ́jẹ̀ẹ́ láti di Násírì. (Nọ́ń. 6:1-21) Òótọ́ ni pé Òfin Mósè tó ní káwọn èèyàn máa jẹ́ irú ẹ̀jẹ́ yìí kò lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀ mọ́. Síbẹ̀, ó ṣeé ṣe kí Pọ́ọ̀lù ronú pé kò sóhun tó burú nínú káwọn ọkùnrin yẹn mú ẹ̀jẹ́ tí wọ́n jẹ́ fún Jèhófà ṣẹ. Torí náà, kò sóhun tó burú bí Pọ́ọ̀lù ṣe bójú tó ìnáwó wọn tó sì tẹ̀ lé wọn. A ò mọ irú ẹ̀jẹ́ tí wọ́n jẹ́ gan-an, àmọ́ èyí ó wù kó jẹ́, kò dájú pé Pọ́ọ̀lù á fọwọ́ sí i pé kí wọ́n fi ẹran rúbọ sí Jèhófà (báwọn Násírì ti máa ń ṣe), torí wọ́n gbà gbọ́ pé ìyẹn á wẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn mọ́. Ẹbọ pípé tí Kristi fi ara rẹ̀ rú ti fòpin sírú àwọn ẹbọ bẹ́ẹ̀ táwọn èèyàn fi ń ṣètùtù. Ohun yòówù kí Pọ́ọ̀lù ṣe, ó dájú pé kò ní gbà láti ṣe ohunkóhun tó lè kó bá ẹ̀rí ọkàn ẹ̀.