Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
e Lọ́dún 49 Sànmánì Kristẹni, nígbà táwọn àpọ́sítélì àtàwọn alágbà ń jíròrò lórí bóyá ó yẹ káwọn Kèfèrí máa tẹ̀ lé Òfin Mósè tàbí kò yẹ, wọ́n pe àwọn Kristẹni kan tó wà níbẹ̀ ní “àwọn kan tó wá látinú ẹ̀ya ìsìn àwọn Farisí, àmọ́ tí wọ́n ti di onígbàgbọ́.” (Ìṣe 15:5) Ó jọ pé ìdí tí wọ́n fi pè wọ́n bẹ́ẹ̀ ni pé Farisí ni wọ́n kí wọ́n tó di Kristẹni.