Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìjọba Ísírẹ́lì tó wà níhà àríwá ni Jèhófà ń bá wí níbí. Àwọn èèyàn ìjọba ẹ̀yà mẹ́wàá yìí ti wà nígbèkùn fún odindi ọgọ́rùn-ún ọdún nígbà tí Jeremáyà jíṣẹ́ yìí fún wọn. Jeremáyà sì sọ pé títí di bóun ṣe ń jíṣẹ́ yẹn, orílẹ̀-èdè yẹn lápapọ̀ ò tíì ronú pìwà dà. (2 Ọba 17:16-18, 24, 34, 35) Àmọ́, ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn lè pa dà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, kí wọ́n sì rí ojú rere rẹ̀ bóyá kí wọ́n tiẹ̀ kúrò nígbèkùn pàápàá.