Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Aísáyà sàsọtẹ́lẹ̀ nípa àwọn tí wọ́n bí ní ìwẹ̀fà àtàwọn tí wọ́n sọ di ìwẹ̀fà, tó jẹ́ pé wọ́n ń bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kópa nínú ìjọsìn déwọ̀n àyè kan nígbà ayé rẹ̀. Ó ní tí wọ́n bá jẹ́ onígbọràn, wọ́n máa jèrè “ohun tí ó sàn ju àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin” lọ, ìyẹn ni pé wọ́n á ní “orúkọ tí yóò wà fún àkókò tí ó lọ kánrin” ní ilé Ọlọ́run.—Aísá. 56:4, 5.