Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ọba gba àwọn Júù láyè láti máa bá ìjà náà lọ lọ́jọ́ kejì kí wọ́n lè rẹ́yìn àwọn ọ̀tá wọn. (Ẹ́sít. 9:12-14) Àwọn Júù ṣì máa ń ṣe ìrántí ìṣẹ́gun yẹn lọ́dọọdún. Ó máa ń jẹ́ ní oṣù Ádárì, èyí tó sábà máa ń bọ́ sí ìparí oṣù February àti ìbẹ̀rẹ̀ oṣù March lóde òní. Wọ́n ń pe ayẹyẹ náà ní Púrímù, ìyẹn orúkọ kèké tí Hámánì ṣẹ́ nígbà tó pète láti pá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì run.