Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
d Jésù tún sọ irú kókó kan náà nínú àkàwé olówò arìnrìn-àjò kan tó lọ wá àwọn péálì tó níye lórí gan-an. Nígbà tí olówò yìí rí péálì náà, ó ta gbogbo ohun tó ní, ó sì rà á. (Mát. 13:45, 46) Àkàwé méjèèjì náà sì tún kọ́ wa pé ó lè jẹ́ ọ̀nà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ la máa gbà kẹ́kọ̀ọ́ nípa òtítọ́ Ìjọba náà. A lè sọ pé ńṣe ni àwọn kan kàn bá òtítọ́ pàdé; ṣe làwọn míì sì wá a kàn. Ṣùgbọ́n ọ̀nà yòówù ká gbà rí òtítọ́, ńṣe la fi tinútinú ṣe gbogbo ohun tó gbà ká lè fi Ìjọba náà sí ipò àkọ́kọ́ ní ìgbésí ayé wa.