Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó ní irú ẹyọ owó tí àwọn Júù tó wá láti ìlú míì gbọ́dọ̀ fi san owó orí ọdọọdún ní tẹ́ńpìlì. Torí náà, àwọn tó ń pààrọ̀ owó ní tẹ́ńpìlì máa ń gba owó lọ́wọ́ wọn kí wọ́n tó lè bá wọn ṣẹ́ ẹyọ owó tí wọ́n ní lọ́wọ́ sí irú owó tí wọ́n lé lò ní tẹ́ńpìlì. Yàtọ̀ síyẹn, ó lè pọn dandan pé káwọn àlejò ra àwọn ẹran tí wọ́n máa fi rúbọ. Ó lè jẹ́ owó gọbọi tí àwọn oníṣòwò náà máa ń fi lé ọjà tàbí iye tí wọ́n ń gbà lọ́wọ́ àwọn èèyàn ló mú kí Jésù pè wọ́n ní “ọlọ́ṣà.”