Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
d Bíbélì tún sọ tẹ́lẹ̀ nípa ìgbéjàkò látọ̀dọ̀ “àwọn ará Ásíríà” òde òní tí wọ́n á wá ọ̀nà láti pa àwọn èèyàn Ọlọ́run rẹ́. (Míkà 5:5) Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ohun kan náà ni ìgbéjàkò mẹ́rin tí Bíbélì lo orúkọ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ fún, tó sì sọ tẹ́lẹ̀ pé ó máa bá àwọn èèyàn Ọlọ́run ń tọ́ka sí, ìyẹn ìgbéjàkò látọ̀dọ̀ Gọ́ọ̀gù ti ilẹ̀ Mágọ́gù, látọ̀dọ̀ ọba àríwá, látọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé àti látọ̀dọ̀ àwọn ará Ásíríà.