Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
d “Títí fi di àkókò òpin” lè túmọ̀sí “nígba àkókò òpin.” Ọ̀rọ̀ náà tí a túmọ̀ sí “títí” níhìn-ín farahàn nínú ọ̀rọ̀-ẹsẹ̀-ìwé èdè Aramaic fún Danieli 7:25 ó sì túmọ̀sí “nígbà” tàbí “fún” níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ náà ní irúfẹ́ ìtumọ̀ kan-náà nínú ọ̀rọ̀-ẹsẹ̀-ìwé èdè Heberu fún 2 Ọba 9:22, Jobu 20:5, àti Awọn Onidajọ 3:26. Bí ó ti wù kí ó rí, nínú ìtumọ̀ Danieli 11:35 tí ó pọ̀ jùlọ, a túmọ̀ rẹ̀ sí “títí,” bí ó bá sì jẹ́ pé èyí ni òye tí ó tọ̀nà, nígbà náà “àkókò òpin” níhìn-ín gbọ́dọ̀ jẹ́ àkókò òpin ìfaradà àwọn ènìyàn Ọlọrun.—Fiwé “Ifẹ Tirẹ Ni Ki A Ṣe Li Aiye,” ojú-ìwé 263.