Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
e Ọ̀pọ̀ rí ìyípadà nínú ìtẹnumọ́ nínú àkọsílẹ̀ Luku lẹ́yìn Luku 21:24. Dókítà Leon Morris sọ pé: “Jesu ń báa lọ láti sọ̀rọ̀ nípa àkókò àwọn Keferi. . . . Gẹ́gẹ́ bí èrò ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀, àfiyèsí ti yí sórí ìpadàbọ̀ Ọmọkùnrin ènìyàn báyìí.” Ọ̀jọ̀gbọ́n R. Ginns kọ̀wé pé: “Ìpadàbọ̀ Ọmọkùnrin Ènìyàn—(Mt 24:29-31; Mk 13:24-27). Mímẹ́nukan ‘àkókò àwọn Keferi’ pèsè ìnasẹ̀-ọ̀rọ̀ fún ẹṣin-ọ̀rọ̀ yìí; ojú-ìwòye [ti Luku] nísinsìnyí ni a mú ríran rékọjá ìparun Jerusalemu wọnú ọjọ́-ọ̀la.”