Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
f Ọ̀jọ̀gbọ́n Walter L. Liefeld kọ̀wé pé: “Ó ṣeéṣe nítòótọ́ láti tànmọ́ọ̀ pé àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Jesu ní àwọn ìpele ìdàgbàsókè méjì nínú: (1) àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ A.D. 70 tí wọ́n wémọ́ tẹmpili náà àti (2) àwọn wọnnì tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú jíjìnnà-réré, tí a fi ọ̀rọ̀ tí ó túbọ̀ jẹ́ ti ìṣípayá ṣàpèjúwe.” Àlàyé-ọ̀rọ̀ tí J. R. Dummelow jẹ́ olùyẹ̀wòṣàtúnṣe fún sọ pé: “Ọ̀pọ̀ nínú àwọn ìṣòro lílekoko inú ọ̀rọ̀-àwíyé ńlá yìí pòórá nígbà tí ó di mímọ̀ pé Oluwa wa kò tọ́ka sí ìṣẹ̀lẹ̀ kanṣoṣo nínú rẹ̀ bíkòṣe méjì, àti pé èyí àkọ́kọ́ jẹ́ àpẹẹrẹ-òjìji fún èyí èkejì. . . . Ní pàtàkì [Luku] 21:24, tí ó sọ̀rọ̀ nípa ‘àkókò àwọn Keferi,’ . . . pààlà àkókò kan tí kò ṣe pàtó sáàárín ìṣubú Jerusalemu àti òpin ayé.”