Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Josephus kọ̀wé nípa àwọn ohun tí ó bẹ̀rẹ̀ sí farahàn láàárín ìgbà tí àwọn ọmọ-ogun Romu kọ́kọ́ kọlu Jerusalemu (66 C.E.) àti ìparun rẹ̀: “Ní ọ̀gànjọ́ òru, ẹ̀fúùfù aṣèparun fẹ́; ìjì-líle jà, àrọ̀ọ̀rọ̀dá òjò rọ̀, mànàmáná ń kọ yẹ̀rìyẹ̀rì láìdáwọ́dúró, sísán ààrá ń kó ìpayà báni, ilẹ̀-ayé mì tìtì pẹ̀lú ariwo tí ń dinilétí. Ní kedere ìwólulẹ̀ gbogbo ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan yìí jẹ́ òjìji ìṣáájú fún ìjábá fún ìran ènìyàn, ẹnikẹ́ni kò sì lè ṣiyèméjì pé àwọn àmì-àpẹẹrẹ náà ń fúnni ní ìkìlọ̀ nípa àjálù kan tí kò ní àfiwé.”