Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ṣugbọn, Jehofa tún ń gbé awọn kókó abájọ mìíràn yẹ̀wò nígbà tí ó bá ń gbèrò yálà lati dáríjini. Fún àpẹẹrẹ, bí olùṣe láìfí kan kò bá mọ awọn ọ̀pá ìdíwọ̀n Ọlọrun, irú àìmọ̀kan bẹ́ẹ̀ lè dín ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ kù. Nígbà tí Jesu rọ Baba rẹ̀ lati dáríji awọn tí ó ṣekú pa á, ó hàn gbangba pé Jesu ń sọ̀rọ̀ nipa awọn ọmọ-ogun Romu tí wọn pa á. Wọn “kò mọ ohun tí wọn ń ṣe,” níwọ̀n bí wọn kò ti mọ ẹni tí ó jẹ́ nítòótọ́. Bí ó ti wù kí ó rí, awọn aṣáájú ìsìn tí wọn wà lẹ́yìn ìṣekúpani naa jẹ̀bi tí ó pọ̀ gan-an—ìdáríjì kò sì ṣeéṣe, fún pupọ lára wọn.—Johannu 11:45-53; fiwé Iṣe 17:30.