Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Nígbà tí ó ṣe, a rí i pé bí a kò bá ní máa ṣayẹyẹ ọjọ́ ìbí tí ó ṣe pàtàkì jùlọ, a kò ní máa ṣayẹyẹ ọjọ́ ìbí kankan. Yàtọ̀ sí ìyẹn, yálà àwọn ọmọ Israeli tàbí àwọn Kristian ìjímìjí kò ṣayẹyẹ ọjọ́ ìbí. Bibeli mẹ́nukan ọjọ́ ìbí méjì péré, ọ̀kan jẹ́ ti Farao èkejì sì jẹ́ ti Herodu Antipa. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ni a fi ìpànìyàn bàjẹ́. Àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa kì í ṣayẹyẹ ọjọ́ ìbí nítorí pé àwọn ayẹyẹ wọ̀nyí pilẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn abọ̀rìṣà ó sì ń gbé ọlọ́jọ́ ìbí ga.—Genesisi 40:20-22; Marku 6:21-28.