Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà kan, Ilé Ìṣọ́ ṣe àlàyé yìí tí ó fi ìjìnlẹ̀ òye hàn pé: “Kò yẹ kí a fi ìgbésí ayé yìí ṣòfò sórí àwọn ohun asán . . . Bí ìgbésí ayé kò bá ju báyìí náà lọ, a jẹ́ wí pé kò ṣe pàtàkì. Ìgbésí ayé yìí dà bíi bọ́ọ̀lù tí a jù sókè, tí kò pẹ́ tí ó fi tún bọ́ sílẹ̀. Ó dà bí òjìji tí ń sáré kọjá lọ, bí òdòdó tí ń rọ, bíi gaga ewé tí a óò gé kúrò, tí yóò sì gbẹ láìpẹ́. . . . Lórí ìwọ̀n ayérayé, gígùn ọjọ́ ayé wa jẹ́ eruku bíńtín. Bí a bá fi àkókò wé odò tí ń ṣàn, ìgbésí ayé wa kò tilẹ̀ tó èékán kan. Dájúdájú, [Sólómọ́nì] tọ̀nà nígbà tí ó ṣàyẹ̀wò ọ̀pọ̀ ìdàníyàn àti ìgbòkègbodò ènìyàn nínú ìgbésí ayé, tí ó sì sọ pé asán ni wọ́n. A kì í pẹ́ kú, ì bá tilẹ̀ dára kání a kò wá rárá, ọ̀kan nínú ọ̀pọ̀ bílíọ̀nù tí ń wá tí ń lọ, tí ọ̀pọ̀ kò tilẹ̀ mọ̀ pé a wá rárá. Ojú ìwòye yìí kì í ṣe ti aṣòfìn-íntótó tàbí ti amúnibanújẹ́ tàbí ti amúnisoríkọ́ tàbí ti amúnigbọ̀n-jìnnìjìnnì. Bí ìgbésí ayé kò bá ju báyìí náà lọ, a jẹ́ pé ojú ìwòyé yìí jẹ́ òtítọ́, òkodoro òtítọ́ pọ́nńbélé, tí ó sì gbéṣẹ́.”—August 1, 1957, ojú ìwé 472 (Gẹ̀ẹ́sì).