Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àwọn olùwádìí kan sọ pé inú ìwé náà, Book of Enoch, tí ìjótìítọ́ rẹ̀ kò dájú ni Júúdà ti fa ọ̀rọ̀ yọ. Ṣùgbọ́n R. C. H. Lenski sọ pé: “Ìbéèrè wa ni pé: ‘Ibo ni ìwé náà, Book of Enoch, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò bára mu yìí ti wá? Àfikún lásán ni ìwé yìí jẹ́, kò sì sí ẹni tí ó mọ ọjọ́ tí a ṣe àwọn apá rẹ̀ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ dájú. . . ; kò sí ẹni tí ó lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé kì í ṣe inú ìwé Júúdà tìkára rẹ̀ ni àwọn ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú rẹ̀ ti wá.”