Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Níbi tí ó bá ti jẹ́ pé àwọn àṣà ìsìnkú ti lè mú ìdánwò lílekoko bá Kristẹni kan, àwọn alàgbà lè mú kí àwọn tí ó ń nàgà fún ìbatisí gbára dì fún ohun tí ń bẹ níwájú. Nígbà tí wọ́n bá ń jókòó pẹ̀lú àwọn ẹni tuntun wọ̀nyí láti jíròrò àwọn ìbéèrè láti inú ìwé náà, Iṣetojọ Lati Ṣaṣepari Iṣẹ-ojiṣẹ Wa, a gbọ́dọ̀ fún àwọn apá náà “Ọkàn, Ẹ̀ṣẹ̀ àti Ikú” àti “Àmúlùmálà-Ìgbàgbọ́,” ní àfiyèsí fínnífínní. Apá méjèèjí ni ó ní àwọn ìbéèrè yàn-bí-o-bá-fẹ́ fún ìjíròrò. Níhìn-ín ni àwọn alàgbà ti lè pèsè ìsọfúnni nípa àwọn àṣà ìsìnkú tí kò bá Ìwé Mímọ́ mu kí ẹni tí ó ń nàgà fún ìbatisí lè mọ ohun tí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ bí ó bá dojú kọ irú ipò bẹ́ẹ̀.