ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

a Àwọn Kristẹni kan tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ ní ọsibítù ti ní láti gbé kókó ti ọlá àṣẹ yìí yẹ̀ wò. Dókítà kan lè ní ọlá àṣẹ láti sọ pé kí aláìsàn lo irú egbòogi kan tàbí kí a lo ọ̀nà kan láti tọ́jú rẹ̀. Kódà, bí aláìsàn náà kò bá bìkítà, báwo ni Kristẹni kan tó jẹ́ dókítà yóò ṣe ṣètò pé kí a fa ẹ̀jẹ̀ síni lára tàbí kí a bá ẹnì kan ṣẹ́yún, tó sì mọ ohun tí Bíbélì sọ lórí irú ọ̀ràn bẹ́ẹ̀? Ní òdìkejì ẹ̀wẹ̀, nọ́ọ̀sì kan tí a gbà sí ọsibítù lè má ní irú ọlá àṣẹ bẹ́ẹ̀. Níbi tó ti ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀, dókítà kan lè sọ pé kí ó yẹ ẹ̀jẹ̀ ẹnì kan wò fún ète kan tàbí kí ó tọ́jú ẹnì kan tó wá ṣẹ́yún. Ní ìbámu pẹ̀lú àpẹẹrẹ tí ó wà nínú 2 Àwọn Ọba 5:17-19, ó lè parí èrò sí pé níwọ̀n bí ṣíṣètò fún ìfàjẹ̀sínilára náà tàbí ṣíṣẹ́yún náà kò ti ti ọwọ́ òun wá, iṣẹ́ àfiṣèrànwọ́ lásán lòun ń ṣe fún aláìsàn náà. Àmọ́ ṣá o, ó ṣì ní láti ro ti ẹ̀rí-ọkàn rẹ̀, nítorí kí ó lè “hùwà níwájú Ọlọ́run pẹ̀lú ẹ̀rí-ọkàn mímọ́ kedere.”—Ìṣe 23:1.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́