Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ ọmọ ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì nì, G. R. Beasley-Murray, sọ pé: “Kò yẹ kí ọ̀rọ̀ náà “ìran yìí” fa ìṣòro fún àwọn alálàyé Bíbélì rárá. Níwọ̀n ìgbà táa ti gbà pé nínú ìtumọ̀ Gíríìkì ìgbàanì genea túmọ̀ sí ìbímọ, irú-ọmọ, tó sì lè wá túmọ̀ sí ìran, . . . nínú ìtumọ̀ [ti Gíríìkì Septuagint] a sábà ń túmọ̀ rẹ̀ sí ọ̀rọ̀ Hébérù náà, dôr, tó túmọ̀ sí sànmánì, sànmánì ìran ènìyàn, tàbí ìran ní ìtumọ̀ ti àwọn alájọgbáyé. . . . Nínú àwọn ọ̀rọ̀ táa sọ pé Jésù sọ, ó dà bí ẹni pé ọ̀rọ̀ náà nítumọ̀ méjì: lọ́nà kan ó máa ń tọ́ka sí àwọn alájọgbáyé rẹ̀, lọ́nà kejì ẹ̀wẹ̀ ó sábà máa ń túmọ̀ sí ọ̀rọ̀ ìbániwí.”