Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ kan sọ pé ọ̀rọ̀ àfiwé tó jẹ̀ ti èdè Hébérù táa lò nínú Míkà 7:18 wá “láti inú ìwà arìnrìn-àjò kan tó kàn ń kọjá lọ ní tirẹ̀, tí kò mọ̀ pé ohun kan wà níbì kan, nítorí tí kò fiyè sí i. Kì í ṣe pé àpèjúwe yìí ń sọ pé, Ọlọ́run kì í kíyè sí ẹ̀ṣẹ̀ téèyàn bá dá o, tàbí pé ó ń fojú kékeré wò ó tàbí pé o kà á sí ohun tí kò tó nǹkan, ṣùgbọ́n ohun tó ń sọ ni pé nínú àwọn ọ̀ràn kan, Ọlọ́run kì í kíyè sí ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú èrò àtifìyàjẹni; nínú irú ipò bẹ́ẹ̀ kò ní fìyà jẹni, ṣe ni yóò dárí jini.”—Onídàájọ́ 3:26; 1 Sámúẹ́lì 16:8.