Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ìgbà táa rí Jésù ọmọ ọdún méjìlá nínú tẹ́ńpìlì la ti sọ̀rọ̀ Jósẹ́fù kẹ́yìn. Kò sí ẹ̀rí tó fi hàn pé Jósẹ́fù wá síbi àsè ìgbéyàwó tó wáyé ní Kánà, nígbà ìbẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òjíṣẹ́ Jésù. (Jòhánù 2:1-3) Ní ọdún 33 Sànmánì Tiwa, Jésù táa kàn mọ́gi sọ fún Jòhánù, àpọ́sítélì rẹ̀ tó fẹ́ràn jọjọ pé, kó máa tọ́jú Màríà. Ká ní Jósẹ́fù ṣì wà láàyè ni, Jésù kò ni sọ bẹ́ẹ̀.—Jòhánù 19:26, 27.