Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nínú ìwé náà, ẹni tó ṣe awúrúju yẹn ṣàpèjúwe ìrísí Jésù, títí kan àwọ̀ irun orí rẹ̀, ti irùngbọ̀n rẹ̀, àti tí ẹyinjú rẹ̀. Atúmọ̀ Bíbélì nì, Edgar J. Goodspeed ṣàlàyé pé awúrúju yìí “wáyé nítorí kí àwọn èèyàn baà lè tẹ́wọ́ gba àpèjúwe tí ayàwòrán náà ṣe nípa ìrísí Jésù nínú ìwé rẹ̀.”