Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Kúlẹ̀kúlẹ̀ kan tún wà tá ò gbọ́dọ̀ di ojú wa sí: Nínú nacimiento àwọn ará Mẹ́síkò yìí, ọmọ yẹn ni wọ́n tọ́ka sí gẹ́gẹ́ bí “Ọlọ́run Ọmọ,” pẹ̀lú èrò náà pé Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ló wá sáyé gẹ́gẹ́ bí ọmọ ọwọ́. Àmọ́, Bíbélì fi Jésù hàn pé ó jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run tí á bí sáyé; òun kọ́ ni Jèhófà, Ọlọ́run Olódùmarè, bẹ́ẹ̀ ni kò sì bá a dọ́gba. Ṣàyẹ̀wò bí èyí ṣe jẹ́ òtítọ́ sí, nínú Lúùkù 1:35; Jòhánù 3:16; 5:37; 14:1, 6, 9, 28; 17:1, 3; 20:17.