Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Bó tilẹ̀ jẹ́ pé nǹkan bíi kìlómítà mẹ́rìndínlógún síhà ìlà oòrùn ni Odò Yúfírétì wà báyìí sí ibi tí ìlú Úrì wà tẹ́lẹ̀, ẹ̀rí fi hàn pé ìhà ìwọ̀ oòrùn ìlú yẹn ni odò náà wà láyé ọjọ́un. Ìyẹn ni wọ́n fi wá sọ lẹ́yìn náà pé Ábúrámù wá láti “ìhà kejì Odò [Yúfírétì].”—Jóṣúà 24:3.