Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ní ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún lẹ́yìn náà, ńṣe ni Aṣunásípálì Kejì, tí í ṣe ọba Ásíríà, to igi sójú Odò Yúfírétì nítòsí Kákémíṣì nígbà tó fẹ́ sọdá rẹ̀. Bíbélì ò sọ bóyá ọgbọ́n kan náà yìí ni Ábúrámù àtàwọn èèyàn rẹ̀ dá nígbà tí wọ́n fẹ́ sọdá odò náà, tàbí ṣe ni wọ́n kàn wọ́ odò náà kọjá.