Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Àwọn olùṣelámèyítọ́ sọ nígbà kan pé Élámù ò fìgbà kan rí ní irú agbára yẹn lágbègbè Ṣínárì, wọ́n ní irọ́ ni ìtàn nípa ogun tí Kedoláómà wá jà. Ìjíròrò nípa ẹ̀rí táa hú jáde nínú ilẹ̀ tó ti àkọsílẹ̀ Bíbélì lẹ́yìn wà nínú Ilé-Ìṣọ́nà, July 1, 1989, ojú ìwé 4 sí 7.