Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Sítéfánù ọmọ ẹ̀yìn pẹ̀lú lo ìsọfúnni tí a kò rí níbòmíì nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù. Ó lò ó nígbà tó ń sọ̀rọ̀ nípa ìmọ̀ ẹ̀kọ́ tí Mósè gbà ní Íjíbítì, jíjẹ́ tó jẹ́ ẹni ogójì ọdún nígbà tó sá fi Íjíbítì sílẹ̀, ogójì ọdún tó fi wà ní ilẹ̀ Mídíánì, àti ipa tí áńgẹ́lì kó nínú títa àtaré Òfin Mósè.—Ìṣe 7:22, 23, 30, 38.