Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Wọn kì í yọ àwọn ọ̀pá náà nínú ihò wọn, kódà nígbà tí Àpótí náà wà lójú kan nínú àgọ́ ìjọsìn. Ìyẹn ló fi jẹ́ pé wọn kì í lo ọ̀pá náà fún nǹkan mìíràn. Bákan náà, ẹnikẹ́ni ò ní fọwọ́ kan Àpótí ọ̀hún; ká ní wọ́n ń yọ àwọn ọ̀pá náà kúrò nínú ihò wọn ni, gbogbo ìgbà tí wọ́n bá fẹ́ gbé e ni wọ́n á máa fọwọ́ kan Àpótí náà nígbà tí wọ́n bá fẹ́ ti àwọn ọ̀pá náà bọnú ihò wọn. Nígbà tí Númérì 4:6 sọ pé ‘kí wọ́n ti ọ̀pá rẹ̀ bọ̀ ọ́,’ bóyá ohun tí ìyẹn túmọ̀ sí ni pé kí wọ́n tún àwọn ọ̀pá náà ṣe, bí wọ́n ti ń múra àtigbé àpótí wíwúwo yìí lọ sí ibùdó tuntun.