Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà tí Gordon D. Fee tó jẹ́ ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì jinlẹ̀ ń sọ èrò tirẹ̀ nípa ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ pé “ìfẹ́ a máa ní ìpamọ́ra àti inú rere,” ó kọ̀wé pé: “Nínú ẹ̀kọ́ Pọ́ọ̀lù, [ìpamọ́ra àti inú rere] jẹ́ ìhà méjèèjì tí Ọlọ́run kọ sí ìran ènìyàn (Róòmù 2:4). Ní apá kan, ìfaradà onífẹ̀ẹ́ tí Ọlọ́run ní ló jẹ́ kó fawọ́ ìbínú rẹ̀ sí àwọn ọlọ̀tẹ̀ ẹ̀dá sẹ́yìn; ní òdì kejì ẹ̀wẹ̀, inú rere rẹ̀ fara hàn nínú ẹgbẹẹgbẹ̀rún ọ̀nà tó gbà ń fi àánú rẹ̀ hàn. Nípa bẹ́ẹ̀, àpèjúwe ìfẹ́ tí Pọ́ọ̀lù ṣe bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú àpèjúwe méjì yìí tó ṣe nípa Ọlọ́run, ẹni tó tipasẹ̀ Kristi fi hàn pé òun jẹ́ onísùúrù àti onínúure sí àwọn tí ìdájọ́ rẹ̀ tọ́ sí.”