Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àwọn tó kọ Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì kò ṣàlàyé Sáàmù kọkànléláàádọ́rùn-ún lọ síbi àsọtẹ́lẹ̀ nípa Mèsáyà. Dájúdájú, Jèhófà jẹ́ ibi ìsádi àti odi agbára fún ọkùnrin náà Jésù Kristi, gan-an gẹ́gẹ́ bí Ó ṣe jẹ́ fún àwọn ẹni àmì òróró ọmọlẹ́yìn Jésù àti àwọn alábàákẹ́gbẹ́ wọn tó ti ya ara wọn sí mímọ́ ní “àkókò òpin” yìí.—Dáníẹ́lì 12:4.