Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Láyé àwọn baba ńlá ìgbàanì, olórí ìdílé kọ̀ọ̀kan ló ń ṣojú ìyàwó àtàwọn ọmọ rẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kódà wọ́n tilẹ̀ ń rú ẹbọ nítorí wọn. (Jẹ́nẹ́sísì 8:20; 46:1; Jóòbù 1:5) Àmọ́, nígbà tí Jèhófà fún wọn ní Òfin, ó yan àwọn ọkùnrin nínú ìdílé Áárónì gẹ́gẹ́ bí àlùfáà kí wọ́n máa rúbọ fáwọn èèyàn náà. Ó jọ pé ńṣe làwọn àádọ́ta-lérúgba náà kò fara mọ́ ìlànà tuntun yìí.