Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù nìkan ló ṣàyọlò ọ̀rọ̀ tá a fà yọ kẹ́yìn yìí tó wà nínú Ìṣe 20:35. Àmọ́ ṣá, ọ̀rọ̀ tó fara pẹ́ ẹ wà nínú àwọn ìwé Ìhìn Rere. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ńṣe ni Pọ́ọ̀lù gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí (bóyá látẹnu ọmọ ẹ̀yìn kan tó gbọ́ nígbà tí Jésù sọ ọ́ tàbí kó gbọ́ ọ látẹnu Jésù lẹ́yìn tá a jí i dìde) tàbí kó jẹ́ pé àtọ̀runwá la ti fi í hàn án.—Ìṣe 22:6-15; 1 Kọ́ríńtì 15:6, 8.