Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó wá hàn kedere nígbẹ̀yìn gbẹ́yín pé Élíábù arẹwà náà kò láwọn ànímọ́ tó yẹ kí ẹni tó tóótun láti jẹ́ ọba Ísírẹ́lì ní. Nígbà tí Gòláyátì, òmìrán ará Filísínì nì sọ pé òun fẹ́ bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì figẹ̀ wọngẹ̀, ńṣe ni ìbẹ̀rùbojo mú Élíábù, àtàwọn ọkùnrin mìíràn ní Ísírẹ́lì.—1 Sámúẹ́lì 17:11, 28-30.