Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà tí Pétérù ṣèbẹ̀wò sí Síríà Áńtíókù, ó gbádùn ìbákẹ́gbẹ́pọ̀ alárinrin tó ní pẹ̀lú àwọn onígbàgbọ́ tí wọ́n jẹ́ Kèfèrí. Àmọ́, nígbà táwọn Kristẹni tó jẹ́ Júù dé láti Jerúsálẹ́mù, Pétérù “wá ń fà sẹ́yìn, ó sì ń ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀, ní ìbẹ̀rù ẹgbẹ́ àwọn tí ó dádọ̀dọ́.” A lè fojú inú wo bó ṣe máa dun àwọn Kèfèrí tó yí padà yẹn tó, nígbà tí àpọ́sítélì tí wọn bọ̀wọ̀ fún gidigidi kọ̀ láti bá wọn jẹun.—Gálátíà 2:11-13.