Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ní ọ̀rúndún kìíní Sànmánì Tiwa, ọmọ Léfì náà Bánábà ta ilẹ̀ tó ní, ó sì fi owó rẹ̀ ṣètọrẹ láti fi ṣèrànwọ́ fáwọn tó jẹ́ aláìní lára àwọn ọmọlẹ́yìn Kristi ní Jerúsálẹ́mù. Ó lè jẹ́ pé Palẹ́sìnì ni ilẹ̀ náà wà tàbí kó wà ní Kípírọ́sì. Ilẹ̀ náà sì ṣeé ṣe kó jẹ́ ilẹ̀ ìsìnkú kan tí Bánábà rà ní àgbègbè Jerúsálẹ́mù.—Ìṣe 4:34-37.