Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn Kristẹni tòótọ́ mọ̀ pé ìjọba èèyàn sábà máa ń hùwà bí ẹranko ẹhànnà, wọ́n ṣì ń fi ara wọn sábẹ́ “àwọn aláṣẹ onípò gíga” gẹ́gẹ́ bí Bíbélì ṣe pa á láṣẹ. (Róòmù 13:1) Àmọ́ bí irú àwọn aláṣẹ bẹ́ẹ̀ bá pàṣẹ pé kí wọ́n ṣe ohun tó ta ko òfin Ọlọ́run, wọ́n á “ṣègbọràn sí Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí olùṣàkóso dípò àwọn ènìyàn.”—Ìṣe 5:29.