Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Nígbà kan báyìí, Pọ́ọ̀lù àtàwọn Kristẹni mẹ́rin lọ sínú tẹ́ńpìlì láti lọ wẹ ara wọn mọ́ lọ́nà ayẹyẹ. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Òfin tó ní káwọn èèyàn máa ṣe bẹ́ẹ̀ kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ mọ́, síbẹ̀ Pọ́ọ̀lù tẹ̀ lé ìmọ̀ràn tí àwọn àgbà ọkùnrin tó wà ní Jerúsálẹ́mù fún un. (Ìṣe 21:23–25) Síbẹ̀ àwọn Kristẹni kan lè sọ pé ní tàwọn o, àwọn ò ní lọ sí tẹ́ńpìlì tàbí káwọn tẹ̀ lé ààtò yẹn. Bí ẹ̀rí ọkàn àwọn èèyàn ṣe ń ṣiṣẹ́ yàtọ̀ síra nígbà yẹn lọ́hùn ún, bẹ́ẹ̀ gan-an ló ṣe rí lónìí.