Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Láwọn àkókò tí wọ́n kọ Bíbélì, ìdí ọlọ ọlọ́wọ́ ni wọ́n ń fi àwọn ọ̀tá tọ́wọ́ bá tẹ̀ sí, irú bó ṣe ṣẹlẹ̀ sí Sámúsìnì àtàwọn ọmọ Ísírẹ́lì mìíràn. (Àwọn Onídàájọ́ 16:21; Ìdárò 5:13) Àwọn obìnrin tó wà lómìnira ara wọn, máa ń fi ọlọ lọ kóró irúgbìn lọ́ọ̀dẹ̀ ọkọ wọn.—Jóòbù 31:10.