Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìwé La Sagrada Escritura—Texto y comentario por profesores de la Compañía de Jesús (Ẹsẹ àti Àlàyé Ìwé Mímọ́ Láti Ọwọ́ Àwọn Ọ̀jọ̀gbọ́n Tó Sọ̀rọ̀ Nípa Jésù) sọ pé “àwọn kan lára àwọn ará Páṣíà, Mídíà àti Kálídíà làwọn Amòye yẹn, wọ́n di ẹgbẹ́ àlùfáà tó ń gbé iṣẹ́ òkùnkùn, iṣẹ́ awòràwọ̀ àti iṣẹ́ ìṣègùn lárugẹ.” Àmọ́ o, ṣáájú ọ̀rúndún karùn-ún ni àwọn èèyàn ti sọ àwọn Amòye tó lọ sọ́dọ̀ Jésù nígbà tó wà lọ́mọ ọwọ́ di ẹni mímọ́, wọ́n sì fún ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn amòye náà lórúkọ. Orúkọ tí wọ́n fún wọn rèé: Melchior, Gaspar, àti Balthasar. Àwọn èèyàn sọ pé inú kàtídírà tó wà nílùú Cologne, lórílẹ̀-èdè Jámánì ni wọ́n tọ́jú òkú àwọn Amòye náà sí.