Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìwé tó ń ṣàlàyé Bíbélì tí wọ́n pè ní The Holy Bible, With an Explanatory and Critical Commentary, tí F. C. Cook ṣàtúnṣe rẹ̀, ṣàlàyé bí wọ́n ṣe máa ń fi ife woṣẹ́ láyé ìgbàanì, ó sọ pé: “Wọ́n máa ń ṣe é yálà nípa jíju wúrà, fàdákà tàbí òkúta iyebíye sínú omi, lẹ́yìn náà, wọ́n á yẹ irú àwọ̀ tó mú jáde wò; tàbí kí wọ́n kàn wo inú omi náà bí ẹni wo jígí.” Ọ̀gbẹ́ni Christopher Wordsworth tó máa ń ṣàlàyé Bíbélì sọ pé: “Nígbà mìíràn, wọ́n á da omi sínú ife náà, wọ́n á sì rí ìdáhùn nínú àwòrán tí oòrùn tó tàn sórí omi inú ife náà bá mú jáde.”