Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Dáfídì Ọba gba ìlú olódi tó wà lórí Òkè Ńlá Síónì ti orí ilẹ̀ ayé mọ́ àwọn ará Jébúsì lọ́wọ́, ó sì sọ ọ́ di olú ìlú ìjọba rẹ̀. (2 Sámúẹ́lì 5:6, 7, 9) Ó tún gbé Àpótí mímọ́ náà wá síbẹ̀. (2 Sámúẹ́lì 6:17) Níwọ̀n bí Àpótí náà ti jẹ́ ẹ̀rí pé Ọlọ́run wà níbẹ̀, Bíbélì pe Síónì ní ibi tí Ọlọ́run ń gbé, èyí sì mú kí Síónì jẹ́ ohun tó dára láti fi ṣàpẹẹrẹ ọ̀run.—Ẹ́kísódù 25:22; Léfítíkù 16:2; Sáàmù 9:11; Ìṣípayá 11:19.