Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Àwọn ẹ̀dà Bíbélì Almeida tí wọ́n ti ṣe tipẹ́ pe Almeida ní Padre, ìyẹn Fadá, èyí sì mú káwọn kan gbà pé ó ti ṣe àlùfáà ìjọ Kátólíìkì rí. Àmọ́ àwọn ọmọ ilẹ̀ Netherlands tó ṣàtúnṣe sí Bíbélì Almeida ló ṣàṣìṣe, wọ́n rò pé oyè táwọn pásítọ̀ tàbí òjíṣẹ́ máa ń lò ni.