Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìwé Mímọ́ lo “ìmọ́lẹ̀” lọ́nà àpẹẹrẹ láwọn ọ̀nà mélòó kan. Bí àpẹẹrẹ, Bíbélì sọ pé Ọlọ́run jẹ́ ìmọ́lẹ̀. (Sáàmù 104:1, 2; 1 Jòhánù 1:5) Ìwé Mímọ́ fi àwọn nǹkan tá a mọ̀ nípa Ọlọ́run àtàwọn ohun tó fẹ́ ṣe tá a rí nínú Ọ̀rọ̀ rẹ̀ wé ìmọ́lẹ̀. (Aísáyà 2:3-5; 2 Kọ́ríńtì 4:6) Ìmọ́lẹ̀ ni Jésù jẹ́ nígbà tó ń ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé. (Jòhánù 8:12; 9:5; 12:35) Jésù sì pàṣẹ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé kí wọ́n jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ wọn máa tàn.—Mátíù 5:14, 16.