Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nínú àdúrà Kádíṣì táwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ máa ń gbà, wọ́n ń bẹ̀bẹ̀ pé kí orúkọ Ọlọ́run di mímọ́, bí àdúrà tí Jésù kọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ náà ṣe sọ. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn kan ń jiyàn lórí bóyá àdúrà Kádíṣì ti wà láti àkókò Kristi tàbí pé ó ti wà ṣáájú ìgbà yẹn, kò yẹ kó yà wá lẹ́nu pé àdúrà méjèèjì jọ ara wọn. Jésù ò fi àdúrà yẹn kọ́ àwọn èèyàn ní nǹkan tuntun tàbí nǹkan táwọn èèyàn ò gbọ́ rí. Gbogbo ohun tí Jésù tọrọ nínú àdúrà náà jẹ́ àwọn nǹkan tó wà nínú Ìwé Mímọ́ tó wà fún gbogbo àwọn Júù lákòókò yẹn. Ńṣe ni Jésù ń gba àwọn Júù bíi tiẹ̀ níyànjú nípa àwọn nǹkan tó ti yẹ kí wọ́n máa fi sínú àdúrà wọn, àní kí Jésù tó wá sáyé pàápàá.