Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Wo ìyàtọ̀ tó wà láàárín ìrìn àjò tó wà nínú Lúùkù 2:4, 5 àtèyí tí Màríà lọ ṣáájú èyí, Bíbélì sọ pé: “Màríà dìde . . . ó sì lọ” ṣèbẹ̀wò sọ́dọ̀ Èlísábẹ́tì. (Lúùkù 1:39) Lákòókò yẹn, òótọ́ ni pé àdéhùn ti wà láàárín Màríà àti Jósẹ́fù àmọ́ wọn ò tíì ṣègbéyàwó, torí náà Màríà lè lọ láìsọ fún Jósẹ́fù. Lẹ́yìn táwọn méjèèjì ti fẹ́ra wọn sílé, Jósẹ́fù ló pinnu ìrìn àjò tí wọ́n lọ, kì í ṣe Màríà.