Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Àpẹẹrẹ míì nípa bí Ọlọ́run ṣe darí àwọn oníwàásù wà nínú Ìṣe 16:6-10. A rí i kà níbẹ̀ pé “ẹ̀mí mímọ́ ka sísọ ọ̀rọ̀ náà ní àgbègbè Éṣíà [àti Bítíníà] léèwọ̀” fún Pọ́ọ̀lù àtàwọn tí wọ́n jọ ń wàásù. Wọ́n wá gba ìtọ́ni pé ìlú Makedóníà ni kí wọ́n ti lọ wàásù, tí ọ̀pọ̀ ọlọ́kàn tútù èèyàn sì gba ìhìn rere náà gbọ́.